Add parallel Print Page Options

Ṣí àwọn èdìdì ìwé náà

Èmi sì rí i nígbà tí Ọ̀dọ́-àgùntàn náà ṣí ọkàn nínú èdìdì wọ̀nyí, mo sì gbọ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà ń wí bí sísán àrá pé, “Wá, wò ó!” (A)Mo sì wò ó, kíyèsi i, ẹṣin funfun kan: ẹni tí ó sì jókòó lórí i rẹ̀ ní ọfà kan; a sì fi adé kan fún un: ó sì jáde lọ láti ìṣẹ́gun dé ìṣẹ́gun.

Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kejì, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè wí pé, “Wá, wò ó!” Ẹṣin mìíràn tí ó pupa sì jáde: a sì fi agbára fún ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀, láti gba àlàáfíà kúrò lórí ilẹ̀ ayé, àti pé kí wọn kí ó máa pa ara wọn: A sì fi idà ńlá kan lé e lọ́wọ́.

Nígbà tí ó sì di èdìdì kẹta, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kẹta wí pé, “Wá wò ó”. Mo sì wò ó, sì kíyèsi i, ẹṣin dúdú kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ní ìwọ̀n aláwẹ́ méjì ní ọwọ́ rẹ̀. (B)Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn kan ní àárín àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rẹ̀ẹ̀rin nì ti ń wí pé, òṣùwọ̀n alikama kan fún owó idẹ kan, àti òṣùwọ̀n ọkà barle mẹ́ta fún owó idẹ kan, sì kíyèsi i, kí ó má sì ṣe pa òróró àti ọtí wáìnì lára.

Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹrin, mo gbọ́ ohùn ẹ̀dá alààyè kan wí pé, Wá wò ó. (C)Mo sì wò ó, kíyèsi, ẹṣin ràndànràndàn kan: orúkọ ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni ikú, àti ipò òkú sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn. A sì fi agbára fún wọn lórí ìdámẹ́rin ayé, láti fi idà, àti ebi, àti ikú, àti ẹranko lu orí ilẹ̀ ayé pa.

Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì karùn-ún, mo rí lábẹ́ pẹpẹ, ọkàn àwọn tí a ti pa nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí tí wọ́n dìímú: 10 (D)Wọ́n kígbe ní ohùn rara, wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa Olódùmarè, ẹni mímọ́ àti olóòtítọ́ ìwọ kì yóò ṣe ìdájọ́ kí o sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ wa mọ́ lára àwọn tí ń gbé orí ilẹ̀ ayé?” 11 A sì fi aṣọ funfun fún gbogbo wọn; a sì wí fún wọn pé, kí wọn kí ó sinmi fún ìgbà díẹ̀ ná, títí iye àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wọn àti arákùnrin wọn tí a o pa bí wọn, yóò fi dé.

12 (E)Nígbà tí ó sì ṣí èdìdì kẹfà mo sì rí i, sì kíyèsi i, ìṣẹ̀lẹ̀ ńlá kan ṣẹ̀; oòrùn sì dúdú bí aṣọ ọ̀fọ̀ onírun, òṣùpá sì dàbí ẹ̀jẹ̀; 13 (F)àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run sì ṣubú sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí ń rẹ̀ àìgbó èso rẹ̀ dànù, nígbà tí ẹ̀fúùfù ńlá bá mì í. 14 A sì ká ọ̀run kúrò bí ìwé tí a ká, àti olúkúlùkù òkè àti erékùṣù ní a sì ṣí kúrò ní ipò wọn.

15 (G)Àwọn ọba ayé àti àwọn ọlọ́lá àti àwọn olórí ogun, àti àwọn ọlọ́rọ̀ àti àwọn alágbára, àti olúkúlùkù ẹrú, àti olúkúlùkù òmìnira, sì fi ara wọn pamọ́ nínú ihò ilẹ̀, àti nínú àpáta orí òkè; 16 (H)Wọ́n sì ń wí fún àwọn òkè àti àwọn àpáta náà pé, “Ẹ wó lù wá, kí ẹ sì fi wá pamọ́ kúrò lójú ẹni tí ó jókòó lórí ìtẹ́, àti kúrò nínú ìbínú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà: 17 (I)Nítorí ọjọ́ ńlá ìbínú wọn dé; ta ni sì le dúró?”

The Seals

I watched as the Lamb(A) opened the first of the seven seals.(B) Then I heard one of the four living creatures(C) say in a voice like thunder,(D) “Come!” I looked, and there before me was a white horse!(E) Its rider held a bow, and he was given a crown,(F) and he rode out as a conqueror bent on conquest.(G)

When the Lamb opened the second seal, I heard the second living creature(H) say, “Come!” Then another horse came out, a fiery red one.(I) Its rider was given power to take peace from the earth(J) and to make people kill each other. To him was given a large sword.

When the Lamb opened the third seal, I heard the third living creature(K) say, “Come!” I looked, and there before me was a black horse!(L) Its rider was holding a pair of scales in his hand. Then I heard what sounded like a voice among the four living creatures,(M) saying, “Two pounds[a] of wheat for a day’s wages,[b] and six pounds[c] of barley for a day’s wages,[d](N) and do not damage(O) the oil and the wine!”

When the Lamb opened the fourth seal, I heard the voice of the fourth living creature(P) say, “Come!” I looked, and there before me was a pale horse!(Q) Its rider was named Death, and Hades(R) was following close behind him. They were given power over a fourth of the earth to kill by sword, famine and plague, and by the wild beasts of the earth.(S)

When he opened the fifth seal, I saw under(T) the altar(U) the souls of those who had been slain(V) because of the word of God(W) and the testimony they had maintained. 10 They called out in a loud voice, “How long,(X) Sovereign Lord,(Y) holy and true,(Z) until you judge the inhabitants of the earth(AA) and avenge our blood?”(AB) 11 Then each of them was given a white robe,(AC) and they were told to wait a little longer, until the full number of their fellow servants, their brothers and sisters,[e] were killed just as they had been.(AD)

12 I watched as he opened the sixth seal. There was a great earthquake.(AE) The sun turned black(AF) like sackcloth(AG) made of goat hair, the whole moon turned blood red, 13 and the stars in the sky fell to earth,(AH) as figs drop from a fig tree(AI) when shaken by a strong wind. 14 The heavens receded like a scroll being rolled up,(AJ) and every mountain and island was removed from its place.(AK)

15 Then the kings of the earth, the princes, the generals, the rich, the mighty, and everyone else, both slave and free,(AL) hid in caves and among the rocks of the mountains.(AM) 16 They called to the mountains and the rocks, “Fall on us(AN) and hide us[f] from the face of him who sits on the throne(AO) and from the wrath of the Lamb! 17 For the great day(AP) of their[g] wrath has come, and who can withstand it?”(AQ)

Footnotes

  1. Revelation 6:6 Or about 1 kilogram
  2. Revelation 6:6 Greek a denarius
  3. Revelation 6:6 Or about 3 kilograms
  4. Revelation 6:6 Greek a denarius
  5. Revelation 6:11 The Greek word for brothers and sisters (adelphoi) refers here to believers, both men and women, as part of God’s family; also in 12:10; 19:10.
  6. Revelation 6:16 See Hosea 10:8.
  7. Revelation 6:17 Some manuscripts his