Add parallel Print Page Options

Ìtẹ́ Ọ̀run

(A)Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí èmi wò, sì kíyèsi i, ìlẹ̀kùn kan ṣí sílẹ̀ ní ọ̀run: Ohùn kìn-ín-ní tí mo gbọ́ bí ohùn ìpè tí ń bá mi sọ̀rọ̀, tí ó wí pé, “Gòkè wá níhìn-ín, èmi ó sì fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn èyí hàn ọ́.” (B)Lójúkan náà, mo sì wà nínú Ẹ̀mí: sì kíyèsi i, a tẹ́ ìtẹ́ kan ní ọ̀run, ẹnìkan sì jókòó lórí ìtẹ́ náà. Ẹni tí ó sì jókòó náà dàbí òkúta jasperi àti kaneliani lójú. Ni àyíká ìtẹ́ náà ni òṣùmàrè kan wà tí ó dàbí òkúta emeradi lójú. Yí ìtẹ́ náà ká sì ni ìtẹ́ mẹ́rìnlélógún mìíràn; àti lórí àwọn ìtẹ́ náà mo rí àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún jókòó, tí a wọ̀ ni aṣọ àlà; adé wúrà sì wà ni orí wọn. (C)Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni ìró mọ̀nàmọ́ná àti ohùn àti àrá ti jáde wá: níwájú ìtẹ́ náà ni fìtílà iná méje sì ń tàn, èyí tí ń ṣe Ẹ̀mí méje ti Ọlọ́run. (D)Àti láti ibi ìtẹ́ náà ni òkun bi dígí wà tí o dàbí kristali.

Àti yí ìtẹ́ náà ká ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan ni ẹ̀dá alààyè mẹ́rin tí ó kún fún ojú níwájú àti lẹ́yìn wọn. (E)Ẹ̀dá kìn-ín-ní sì dàbí kìnnìún, ẹ̀dá kejì si dàbí ọmọ màlúù, ẹ̀dá kẹta sì ni ojú bi ti ènìyàn, ẹ̀dá kẹrin sì dàbí idì tí ń fò. (F)Àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà, tí olúkúlùkù wọn ni ìyẹ́ mẹ́fà, kún fún ojú yíká ara àti nínú; wọn kò sì sinmi lọ́sàn àti lóru, láti wí pé:

“Mímọ́, mímọ́, mímọ́,
Olúwa Ọlọ́run Olódùmarè,
tí ó ti wà, tí ó sì ń bẹ, tí ó sì ń bọ̀ wá!”

(G)Nígbà tí àwọn ẹ̀dá alààyè náà bá sì fi ògo àti ọlá, àti ọpẹ́ fún ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, tí o ń bẹ láààyè láé àti láéláé. 10 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà yóò sì wólẹ̀ níwájú ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́, wọn yóò sì tẹríba fún ẹni tí ń bẹ láààyè láé àti láéláé, wọn yóò sì fi adé wọn lélẹ̀ níwájú ìtẹ́ náà, wí pé:

11 “Olúwa àti Ọlọ́run, ìwọ ni o yẹ,
láti gba ògo àti ọlá àti agbára:
nítorí pé ìwọ ni o dá ohun gbogbo,
    àti nítorí ìfẹ́ inú rẹ̀ ni
    wọn fi wà tí a sì dá wọn.”

The Throne in Heaven

After this I looked, and there before me was a door standing open(A) in heaven. And the voice I had first heard speaking to me like a trumpet(B) said, “Come up here,(C) and I will show you what must take place after this.”(D) At once I was in the Spirit,(E) and there before me was a throne in heaven(F) with someone sitting on it. And the one who sat there had the appearance of jasper(G) and ruby.(H) A rainbow(I) that shone like an emerald(J) encircled the throne. Surrounding the throne were twenty-four other thrones, and seated on them were twenty-four elders.(K) They were dressed in white(L) and had crowns of gold on their heads. From the throne came flashes of lightning, rumblings and peals of thunder.(M) In front of the throne, seven lamps(N) were blazing. These are the seven spirits[a](O) of God. Also in front of the throne there was what looked like a sea of glass,(P) clear as crystal.

In the center, around the throne, were four living creatures,(Q) and they were covered with eyes, in front and in back.(R) The first living creature was like a lion, the second was like an ox, the third had a face like a man, the fourth was like a flying eagle.(S) Each of the four living creatures(T) had six wings(U) and was covered with eyes all around,(V) even under its wings. Day and night(W) they never stop saying:

“‘Holy, holy, holy

is the Lord God Almighty,’[b](X)

who was, and is, and is to come.”(Y)

Whenever the living creatures give glory, honor and thanks to him who sits on the throne(Z) and who lives for ever and ever,(AA) 10 the twenty-four elders(AB) fall down before him(AC) who sits on the throne(AD) and worship him who lives for ever and ever. They lay their crowns before the throne and say:

11 “You are worthy, our Lord and God,
    to receive glory and honor and power,(AE)
for you created all things,
    and by your will they were created
    and have their being.”(AF)

Footnotes

  1. Revelation 4:5 That is, the sevenfold Spirit
  2. Revelation 4:8 Isaiah 6:3