Add parallel Print Page Options

Àwọn ẹlẹ́rìí méjì

11 (A)A sì fi ìfèéfèé kan fún mi tí o dàbí ọ̀pá-ìwọ̀n: ẹnìkan sì wí pé, “Dìde, wọn tẹmpili Ọlọ́run, àti pẹpẹ, àti àwọn tí ń sìn nínú rẹ̀. (B)Sì fi àgbàlá tí ń bẹ lóde tẹmpili sílẹ̀, má sì ṣe wọ́n ọ́n; nítorí tí a fi fún àwọn aláìkọlà: ìlú mímọ́ náà ni wọn ó sì tẹ̀ mọ́lẹ̀ ní oṣù méjìlélógójì. Èmi ó sì yọ̀ǹda fún àwọn ẹlẹ́rìí mi méjèèje, wọn ó sì sọtẹ́lẹ̀ fún ẹgbẹ̀fà ọjọ́ ó-lé-ọgọ́ta nínú aṣọ ọ̀fọ̀.” (C)Wọ̀nyí ni igi olifi méjì náà, àti ọ̀pá fìtílà méjì náà tí ń dúró níwájú Olúwa ayé. (D)Bí ẹnikẹ́ni bá sì fẹ́ pa wọn lára, iná ó ti ẹnu wọn jáde, a sì pa àwọn ọ̀tá wọn run: báyìí ni a ó sì pa ẹnikẹ́ni tí ó ba ń fẹ́ pa wọn lára run. (E)Àwọn wọ̀nyí ni ó ni agbára láti sé ọ̀run, tí òjò kò fi lè rọ̀ ni ọjọ́ àsọtẹ́lẹ̀ wọn: Wọ́n sì ní agbára lórí omi láti sọ wọn di ẹ̀jẹ̀, àti láti fi onírúurú àjàkálẹ̀-ààrùn kọlu ayé, nígbàkúgbà tí wọ́n bá fẹ́.

(F)Nígbà tí wọn bá sì ti parí ẹ̀rí wọn, ẹranko tí o ń tí inú ọ̀gbun gòkè wá yóò bá wọn jagun, yóò sì ṣẹ́gun wọn, yóò sì pa wọ́n. (G)Òkú wọn yóò sì wà ni ìgboro ìlú ńlá náà tí a ń pè ní Sodomu àti Ejibiti nípa ti ẹ̀mí, níbi tí a gbé kan Olúwa wọ́n mọ́ àgbélébùú. Fún ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ ni àwọn ènìyàn nínú ènìyàn gbogbo àti ẹ̀yà, àti èdè, àti orílẹ̀, wo òkú wọn, wọn kò si jẹ kì a gbé òkú wọn sínú ibojì. 10 Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró.

11 (H)Àti lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí ìyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹsẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn. 12 (I)Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀; lójú àwọn ọ̀tá wọn.

13 Ní wákàtí náà omìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ́wàá ìlú náà sì wó, àti nínú omìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.

14 Ègbé kejì kọjá; sì kíyèsi i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.

Ìpè méje

15 (J)Angẹli keje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé,

“Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kristi rẹ̀;
    òun yóò sì jẹ ọba láé àti láéláé!”

16 Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run, 17 wí pé:

“Àwa fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa Ọlọ́run, Olódùmarè,
    tí ń bẹ, tí ó sì ti wà,
nítorí pé ìwọ ti gba agbára ńlá rẹ̀,
    ìwọ sì ti jẹ ọba.
18 (K)Inú bí àwọn orílẹ̀-èdè, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ̀ ti dé,
àti àkókò láti dá àwọn òkú lẹ́jọ́,
    àti láti fi èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì,
àti àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn tí o bẹ̀rù orúkọ rẹ̀,
    àti ẹni kékeré àti ẹni ńlá;
àti láti run àwọn tí ń pa ayé run.”

19 (L)A sì ṣí tẹmpili Ọlọ́run sílẹ̀ ní ọ̀run, a sì ri àpótí májẹ̀mú nínú tẹmpili rẹ̀. Mọ̀nàmọ́ná sì kọ, a sì gbọ́ ohùn, àrá sì sán, ilẹ̀ sì mi, yìnyín ńlá sì bọ́.

The Two Witnesses

11 I was given a reed like a measuring rod(A) and was told, “Go and measure the temple of God and the altar, with its worshipers. But exclude the outer court;(B) do not measure it, because it has been given to the Gentiles.(C) They will trample on the holy city(D) for 42 months.(E) And I will appoint my two witnesses,(F) and they will prophesy for 1,260 days,(G) clothed in sackcloth.”(H) They are “the two olive trees”(I) and the two lampstands, and “they stand before the Lord of the earth.”[a](J) If anyone tries to harm them, fire comes from their mouths and devours their enemies.(K) This is how anyone who wants to harm them must die.(L) They have power to shut up the heavens(M) so that it will not rain during the time they are prophesying;(N) and they have power to turn the waters into blood(O) and to strike the earth with every kind of plague as often as they want.

Now when they have finished their testimony, the beast(P) that comes up from the Abyss(Q) will attack them,(R) and overpower and kill them. Their bodies will lie in the public square of the great city(S)—which is figuratively called Sodom(T) and Egypt—where also their Lord was crucified.(U) For three and a half days some from every people, tribe, language and nation(V) will gaze on their bodies and refuse them burial.(W) 10 The inhabitants of the earth(X) will gloat over them and will celebrate by sending each other gifts,(Y) because these two prophets had tormented those who live on the earth.

11 But after the three and a half days(Z) the breath[b] of life from God entered them,(AA) and they stood on their feet, and terror struck those who saw them. 12 Then they heard a loud voice from heaven saying to them, “Come up here.”(AB) And they went up to heaven in a cloud,(AC) while their enemies looked on.

13 At that very hour there was a severe earthquake(AD) and a tenth of the city collapsed. Seven thousand people were killed in the earthquake, and the survivors were terrified and gave glory(AE) to the God of heaven.(AF)

14 The second woe has passed; the third woe is coming soon.(AG)

The Seventh Trumpet

15 The seventh angel sounded his trumpet,(AH) and there were loud voices(AI) in heaven, which said:

“The kingdom of the world has become
    the kingdom of our Lord and of his Messiah,(AJ)
    and he will reign for ever and ever.”(AK)

16 And the twenty-four elders,(AL) who were seated on their thrones before God, fell on their faces(AM) and worshiped God, 17 saying:

“We give thanks(AN) to you, Lord God Almighty,(AO)
    the One who is and who was,(AP)
because you have taken your great power
    and have begun to reign.(AQ)
18 The nations were angry,(AR)
    and your wrath has come.
The time has come for judging the dead,(AS)
    and for rewarding your servants the prophets(AT)
and your people who revere your name,
    both great and small(AU)
and for destroying those who destroy the earth.”

19 Then God’s temple(AV) in heaven was opened, and within his temple was seen the ark of his covenant.(AW) And there came flashes of lightning, rumblings, peals of thunder,(AX) an earthquake and a severe hailstorm.(AY)

Footnotes

  1. Revelation 11:4 See Zech. 4:3,11,14.
  2. Revelation 11:11 Or Spirit (see Ezek. 37:5,14)