1 Kronika 16:23-33
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
23 (A)Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé;
ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
24 Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
25 Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ Jùlọ;
òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
26 Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà,
ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
27 Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀;
agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
28 Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè,
ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
29 Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀;
gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀.
Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
30 Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé!
Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
31 Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn;
Jẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
32 Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀;
Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
33 Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin,
Wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa,
nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.