陶器的比喻

18 耶和华对耶利米说: “你去陶匠家,在那里我有话告诉你。” 我便到陶匠家,见他正用轮盘做器皿。 每当他手中的器皿做坏了,他就用那块泥重做,想怎么做就怎么做。 这时,耶和华对我说: “以色列人啊,难道我不能像陶匠对待陶泥一样对待你们吗?以色列人啊,你们在我手中就像陶泥在陶匠手中一样。这是耶和华说的。 当我宣布要铲除、推翻、毁灭哪一邦或哪一国的时候, 如果他们悔过自新,我必施怜悯,取消我原本要降给他们的灾祸。 当我宣布要建造、栽培哪一邦或哪一国的时候, 10 如果他们做我视为恶的事,不听从我的话,我必改变心意,取消我原本要赐给他们的福气。 11 因此,你去告诉犹大人和耶路撒冷的居民,‘耶和华说,我正计划降灾祸惩罚你们。你们要离开罪恶,改邪归正。’ 12 他们却说,‘不!我们喜欢随心所欲,为所欲为。’”

13 因此耶和华说:
“你们问问列国,
看看谁曾听过这样的事?
少女般的以色列竟做了一件极可怕的事。
14 黎巴嫩山岭上的积雪会融化吗?
从远方流来的冰凉溪水会停止吗?
15 然而,我的子民却把我抛诸脑后,
向虚无的神明烧香,
偏离古道,在歧途上绊绊跌跌。
16 因此,他们的土地必荒凉,
永远遭人嗤笑,
经过此地的人无不惊惧,
摇头叹息。
17 我要在敌人面前驱散他们,
就像东风吹散尘土一样。
在他们遭难的时候,
我必以背相向,
不理睬他们。”

18 他们说:“来!我们设计对付耶利米吧,反正我们有祭司教导律法,有智者出谋划策,有先知传讲预言。来吧!我们抨击他,不要理会他的话。”

19 耶和华啊,求你眷顾我,
听听敌人对我的指控。
20 人岂能以恶报善?
他们竟设陷阱谋害我,
求你回想我怎样站在你面前为他们求情,
怎样求你不要向他们发烈怒。
21 因此,愿他们丧身刀下,
儿女饿死,
妻子丧夫亡子,
年长的被杀,
年少的死于战场!
22 当你使敌军突袭他们时,
愿他们家中传出哭喊声,
因为他们挖陷阱要捕捉我,
设圈套要绊我的脚。
23 耶和华啊,你知道他们害我的各种诡计,
求你不要赦免他们的罪过,
不要饶恕他们的恶行。
求你使他们倒在你面前,
求你在烈怒中惩罚他们。

Ní ilé amọ̀kòkò

18 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe: “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.” Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́. Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.

Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé: (A)“Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli. Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun. Tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn. Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan. 10 Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.

11 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’ 12 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’ ”

13 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí:

“Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè,
    ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri?
    Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
14 Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni
    yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta?
Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù,
    tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
15 Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi,
    wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán,
tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn,
    àti ọ̀nà wọn àtijọ́.
    Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́,
    àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe
16 Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di
    nǹkan ẹ̀gàn títí láé;
Gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù,
    wọn yóò sì mi orí wọn.
17 Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn,
    Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn.
Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn
    ní ọjọ́ àjálù wọn.”

18 Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”

19 Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun

    tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
20 Ṣe kí a fi rere san búburú?
    Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi,
rántí pé mo dúró níwájú rẹ,
    mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti
    yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
21 Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn
    jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà
jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó
    jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn
kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin
    wọn lójú ogun.
22 Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn
    nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun
kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́
    kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi
23 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ
    gbogbo ète wọn láti pa mí,
má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n
    bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ.
    Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.