Add parallel Print Page Options

责其辜负主恩

11 以色列年幼的时候,我爱他,就从埃及召出我的儿子来。 先知越发招呼他们,他们越发走开,向诸巴力献祭,给雕刻的偶像烧香。 我原教导以法莲行走,用膀臂抱着他们,他们却不知道是我医治他们。 我用慈[a]绳爱索牵引他们,我待他们如人放松牛的两腮夹板,把粮食放在他们面前。

必遭重罚

“他们必不归回埃及地,亚述人却要做他们的王,因他们不肯归向我。 刀剑必临到他们的城邑,毁坏门闩,把人吞灭,都因他们随从自己的计谋。 我的民偏要背道离开我,众先知虽然招呼他们归向至上的主,却无人尊崇主。

仍施矜恤

以法莲哪,我怎能舍弃你?以色列啊,我怎能弃绝你?我怎能使你如押玛?怎能使你如洗扁?我回心转意,我的怜爱大大发动。 我必不发猛烈的怒气,也不再毁灭以法莲,因我是神,并非世人,是你们中间的圣者,我必不在怒中临到你们。 10 耶和华必如狮子吼叫,子民必跟随他,他一吼叫,他们就从西方急速而来。 11 他们必如雀鸟从埃及急速而来,又如鸽子从亚述地来到,我必使他们住自己的房屋。这是耶和华说的。

12 以法莲用谎话,以色列家用诡计围绕我,犹大却靠神掌权,向圣者有忠心[b]

Footnotes

  1. 何西阿书 11:4 “慈”原文作“人的”。
  2. 何西阿书 11:12 或作:犹大向神,向诚实的圣者犹疑不定。

Ìfẹ́ Ọlọ́run sí Israẹli

11 (A)“Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀,
    mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
Bí a ti ń pe wọn,
    bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi,
wọn rú ẹbọ sí Baali,
    wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn
    mo di wọ́n mú ní apá,
ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀
    pé mo ti mú wọn láradá.
Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n
    àti ìdè ìfẹ́.
Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn
    Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.

“Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí
    Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí
    nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn
    yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́
    yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi
bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ,
    kò ní gbé wọn ga rárá.

“Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu?
    Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli
Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma?
    Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ṣeboimu?
Ọkàn mi yípadà nínú mi
    àánú mi sì ru sókè
Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ,
    tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro.
Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn
    Ẹni mímọ́ láàrín yín,
    Èmi kò ní í wá nínú ìbínú
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa;
    òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún
Nígbà tó bá bú
    àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù
    bí i ẹyẹ láti Ejibiti
    bí i àdàbà láti Asiria
Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,”
    ni Olúwa wí.

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli

12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká
    ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn.
Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run
    Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.