Add parallel Print Page Options

Ìfẹ́ Ọlọ́run sí Israẹli

11 (A)“Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀,
    mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
Bí a ti ń pe wọn,
    bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi,
wọn rú ẹbọ sí Baali,
    wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn
    mo di wọ́n mú ní apá,
ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀
    pé mo ti mú wọn láradá.
Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n
    àti ìdè ìfẹ́.
Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn
    Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.

“Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí
    Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí
    nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn
    yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́
    yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi
bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ,
    kò ní gbé wọn ga rárá.

“Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu?
    Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli
Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma?
    Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ṣeboimu?
Ọkàn mi yípadà nínú mi
    àánú mi sì ru sókè
Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ,
    tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro.
Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn
    Ẹni mímọ́ láàrín yín,
    Èmi kò ní í wá nínú ìbínú
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa;
    òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún
Nígbà tó bá bú
    àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù
    bí i ẹyẹ láti Ejibiti
    bí i àdàbà láti Asiria
Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,”
    ni Olúwa wí.

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli

12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká
    ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn.
Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run
    Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.