Add parallel Print Page Options

Peteru ṣàlàyé nípa àwọn ìhùwàsí rẹ̀

11 Àwọn aposteli àti àwọn arákùnrin ti ó wà ni Judea sì gbọ́ pé àwọn aláìkọlà pẹ̀lú ti gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Nígbà tí Peteru sì gòkè wá sí Jerusalẹmu, àwọn ti ìkọlà ń bá a wíjọ́ wí pé, “Ìwọ wọlé tọ àwọn ènìyàn aláìkọlà lọ, ó sì bá wọn jẹun.”

(A)Ṣùgbọ́n Peteru bẹ̀rẹ̀ sí là á yé wọn lẹ́sẹẹsẹ, wí pé, “Èmi wà ni ìlú Joppa, mo ń gbàdúrà, mo rí ìran kan lójúran. Ohun èlò kan sọ̀kalẹ̀ bí ewé tákàdá ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá; ó sì wá títí de ọ̀dọ̀ mi. Mo tẹjúmọ́ ọn, mo sì fiyèsí i, mo sí rí ẹran ẹlẹ́ṣẹ̀ mẹ́rin, àti ẹranko igbó, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run. Mo sì gbọ́ ohùn kan ti ó fọ̀ sí mi pé, ‘Dìde, Peteru: máa pa, kí ó sì máa jẹ.’

“Ṣùgbọ́n mo dáhùn wí pé, ‘rara Olúwa! Nítorí ohun èèwọ̀ tàbí ohun aláìmọ́ kan kò wọ ẹnu mi rí láéláé.’

“Ṣùgbọ́n ohùn kan dáhùn nígbà ẹ̀ẹ̀kejì láti ọ̀run wá pé, ‘Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, kí ìwọ má ṣe pè é ní àìmọ́.’ 10 Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà mẹ́ta; a sì tún fa gbogbo rẹ̀ sókè ọ̀run.

11 “Sì wò ó, lójúkan náà ọkùnrin mẹ́ta dúró níwájú ilé ti a gbé wà, ti a rán láti Kesarea sí mi. 12 Ẹ̀mí sì wí fún mi pé, kí èmi bá wọn lọ, ki èmi má ṣe kọminú ohunkóhun. Àwọn arákùnrin mẹ́fà wọ̀nyí sì bá mi lọ, a sì wọ ilé ọkùnrin náà: 13 Ó sì sọ fún wa bí òun ti rí angẹli kan tí ó dúró ní ilé rẹ̀, tí ó sì wí pé, ‘Ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni tí àpèlé rẹ̀ jẹ́ Peteru; 14 ẹni tí yóò sọ ọ̀rọ̀ fún ọ, nípa èyí tí a ó fi gba ìwọ àti gbogbo ilé rẹ là.’

15 “Bí mo sì ti bẹ̀rẹ̀ sì sọ, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti bà lé wa ni àtètèkọ́ṣe. 16 (B)Nígbà náà ni mo rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí pé, ‘Johanu fi omi bamitiisi nítòótọ́; ṣùgbọ́n a ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.’ 17 Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run sì ti fi irú ẹ̀bùn kan náà fún wọn bí ó ti fi fún àwa pẹ̀lú nígbà tí a gba Jesu Kristi Olúwa gbọ́, ta ni èmi tí n ó fi rò pé mo le è de Ọlọ́run ní ọ̀nà?”

18 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́, wọ́n sì yin Ọlọ́run ògo wí pé, “Ǹjẹ́ Ọlọ́run fi ìrònúpìwàdà sí ìyè fún àwọn aláìkọlà pẹ̀lú!”

Ìjọ ní Antioku

19 (C)Nítorí náà àwọn tí a sì túká kiri nípasẹ̀ inúnibíni tí ó dìde ní ti Stefanu, wọ́n rìn títí de Fonisia, àti Saipurọsi, àti Antioku, wọn kò sọ ọ̀rọ̀ náà fún ẹnìkan bí kò ṣe fún kìkì àwọn Júù. 20 Ṣùgbọ́n àwọn kan ń bẹ nínú wọn tí ó jẹ́ ará Saipurọsi àti Kirene; nígbà tí wọ́n dé Antioku, wọ́n sọ̀rọ̀ fún àwọn Helleni pẹ̀lú, wọ́n ń wàásù ìròyìn ayọ̀ nípa Jesu Olúwa. 21 Ọwọ́ Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn: ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì gbàgbọ́, wọ́n sì yípadà sí Olúwa.

22 Ìròyìn nípa wọn sì dé etí ìjọ ti ó wà ni Jerusalẹmu; wọ́n sì rán Barnaba lọ títí dé Antioku; 23 Nígbà ti ó dé ti ó sì rí ẹ̀rí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run, ó yọ̀, ó sì gba gbogbo wọn níyànjú pé, pẹ̀lú ìpinnu ọkàn ni kí wọn fi ara mọ́ Olúwa. 24 Nítorí òun jẹ́ ènìyàn rere, ó sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àti fún ìgbàgbọ́; ènìyàn púpọ̀ ni a sì kà kún Olúwa.

25 Barnaba sì jáde lọ sí Tarsu láti wá Saulu, 26 nígbà tí ó sì rí i, ó mú un wá sí Antioku. Fún ọdún kan gbáko ni wọ́n fi ń bá ìjọ péjọpọ̀, tí wọ́n sì kọ́ ènìyàn púpọ̀. Ní Antioku ni a sì kọ́kọ́ ti pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ni “Kristiani.”

27 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn wòlíì sì ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ wá sí Antioku. 28 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn, ti a ń pè ni Agabu sí dìde, ó ti ipa Ẹ̀mí sọ pé, ìyàn ńlá yóò mú yíká gbogbo ilẹ̀ Romu. (Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà ìṣèjọba Kilaudiu.) 29 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì pinnu, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ ti tó, láti rán ìrànlọ́wọ́ sí àwọn arákùnrin tí ó wà ní Judea. 30 Wọn sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọn sì fi ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí àwọn àgbà láti ọwọ́ Barnaba àti Saulu.

Peter Explains His Actions

11 The apostles and the believers(A) throughout Judea heard that the Gentiles also had received the word of God.(B) So when Peter went up to Jerusalem, the circumcised believers(C) criticized him and said, “You went into the house of uncircumcised men and ate with them.”(D)

Starting from the beginning, Peter told them the whole story: “I was in the city of Joppa praying, and in a trance I saw a vision.(E) I saw something like a large sheet being let down from heaven by its four corners, and it came down to where I was. I looked into it and saw four-footed animals of the earth, wild beasts, reptiles and birds. Then I heard a voice telling me, ‘Get up, Peter. Kill and eat.’

“I replied, ‘Surely not, Lord! Nothing impure or unclean has ever entered my mouth.’

“The voice spoke from heaven a second time, ‘Do not call anything impure that God has made clean.’(F) 10 This happened three times, and then it was all pulled up to heaven again.

11 “Right then three men who had been sent to me from Caesarea(G) stopped at the house where I was staying. 12 The Spirit told(H) me to have no hesitation about going with them.(I) These six brothers(J) also went with me, and we entered the man’s house. 13 He told us how he had seen an angel(K) appear in his house and say, ‘Send to Joppa for Simon who is called Peter. 14 He will bring you a message(L) through which you and all your household(M) will be saved.’

15 “As I began to speak, the Holy Spirit came on(N) them as he had come on us at the beginning.(O) 16 Then I remembered what the Lord had said: ‘John baptized with[a] water,(P) but you will be baptized with[b] the Holy Spirit.’(Q) 17 So if God gave them the same gift(R) he gave us(S) who believed in the Lord Jesus Christ, who was I to think that I could stand in God’s way?”

18 When they heard this, they had no further objections and praised God, saying, “So then, even to Gentiles God has granted repentance that leads to life.”(T)

The Church in Antioch

19 Now those who had been scattered by the persecution that broke out when Stephen was killed(U) traveled as far as Phoenicia, Cyprus and Antioch,(V) spreading the word only among Jews. 20 Some of them, however, men from Cyprus(W) and Cyrene,(X) went to Antioch(Y) and began to speak to Greeks also, telling them the good news(Z) about the Lord Jesus. 21 The Lord’s hand was with them,(AA) and a great number of people believed and turned to the Lord.(AB)

22 News of this reached the church in Jerusalem, and they sent Barnabas(AC) to Antioch. 23 When he arrived and saw what the grace of God had done,(AD) he was glad and encouraged them all to remain true to the Lord with all their hearts.(AE) 24 He was a good man, full of the Holy Spirit(AF) and faith, and a great number of people were brought to the Lord.(AG)

25 Then Barnabas went to Tarsus(AH) to look for Saul, 26 and when he found him, he brought him to Antioch. So for a whole year Barnabas and Saul met with the church and taught great numbers of people. The disciples(AI) were called Christians first(AJ) at Antioch.

27 During this time some prophets(AK) came down from Jerusalem to Antioch. 28 One of them, named Agabus,(AL) stood up and through the Spirit predicted that a severe famine would spread over the entire Roman world.(AM) (This happened during the reign of Claudius.)(AN) 29 The disciples,(AO) as each one was able, decided to provide help(AP) for the brothers and sisters(AQ) living in Judea. 30 This they did, sending their gift to the elders(AR) by Barnabas(AS) and Saul.(AT)

Footnotes

  1. Acts 11:16 Or in
  2. Acts 11:16 Or in